Àwọn Ìwé Mímọ́
Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 2


Ìpín 2

Àwọn ohun tí a fà yọ nínú ìwé ìtàn Joseph Smith ní ṣíṣe àtúnsọ àwọn ọ̀rọ ángẹ́lì Mórónì sí Wòlíì Joseph Smith, nígbàtí ó wà nínú ilé onígi àwọn Smith ní Palmyra, New York, ní ìrọ̀lẹ́ 21 Oṣù Kẹsan 1823. Moroni ni ìkẹhìn nínú àwọn ọ̀pọ̀ ònkọ̀tàn tí wọ́n ti ṣe àkọsílẹ̀ èyí tí ó wà níwájú gbogbo ayé nísisìyí bíi Ìwé ti Mọ́mọ́nì. (Fi wé Málákì 4:5–6; bákannáà àwọn ìpín 27:9; 110:13–16; àti 128:18.)

1, Elijah ni yíò fi oyè-àlùfáà hàn; 2–3, Àwọn ìlérí ti àwọn baba ni a gbìn sínú ọkàn àwọn ọmọ.

Kíyèsíi, èmi yíò fi oyè àlùfáà hàn sí ọ, láti ọwọ́ wòlíì Èlíjàh, ṣaájú bíbọ̀ ọjọ́ nlá àti bíbanilẹ́rù ti Olúwa.

Àti pé òun yíò gbìn sí ọkàn àwọn ọmọ awọn ìlérí tí a ṣe fún àwọn baba, ọkàn ti àwọn ọmọ yíò sì yí sí ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn.

Bí kò bá rí bẹ́ẹ̀, gbogbo ilẹ̀ ayé ni yíò di fífiṣòfò pátápátá ní bíbọ̀ rẹ̀.